
- Tòkunbò Dàda
Lẹ́yìn tí ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Super Eagles ti Nigeria lu ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù ti Benin Republic tán pẹ̀lú àmì ayò mẹ́rin sí òdo lánàá, ṣe ni wọn wá bẹ̀rẹ̀ ìṣirò lójú páálí.
Yorùbá bọ̀ wọ́n ní “àárọ̀ kùtù la ti ńsá imọ̀ gbígbẹ”, sùgbón ṣe ni ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Nigeria fi àárọ̀ wọn sùn bí ẹlẹ́yà, èyí tó fàá tí wọn kò fi lékè ìsọ̀rí kòmẹsẹ̀ẹ́yọ wọ́n.
Ní báyìí, ìjọba ọ̀run ti wá di àfagbárawọ̀; ẹ̀rọ ìṣirò ni wọ́n gbé dání, tí wọ́n ń wòye ọ̀nà tí wọ́n yíò gbà kópa nínú ife-ẹ̀yẹ àgbáyé tó ńbọ̀ yìí.
Ẹ jẹ́ ká máa wo ibi tó máa já sí. Orí òkẹ́rẹ́ koko láwo, táa bá wí fún ọmọ ẹni á gbọ́.
